1. Kor 12:4-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Njẹ onirũru ẹ̀bun li o wà, ṣugbọn Ẹmí kanna ni.

5. Onirũru iṣẹ-iranṣẹ li ó si wà, Oluwa kanna si ni.

6. Onirũru iṣẹ li o si wà, ṣugbọn Ọlọrun kanna ni ẹniti nṣiṣẹ gbogbo wọn ninu gbogbo wọn.

7. Ṣugbọn a nfi ifihàn Ẹmí fun olukuluku enia lati fi jère.

8. Nitoriti a fi ọ̀rọ ọgbọ́n fun ẹnikan nipa Ẹmí; ati fun ẹlomiran ọ̀rọ-ìmọ nipa Ẹmí kanna;

9. Ati fun ẹlomiran igbagbọ́ nipa Ẹmí kanna; ati fun ẹlomiran ẹ̀bun imularada nipa Ẹmí kanna;

1. Kor 12