Esr 9:9-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

9. Nitoripe ẹrú li awa iṣe; ṣugbọn Ọlọrun wa kò kọ̀ wa silẹ li oko ẹrú wa, ṣugbọn o ti nawọ́ ãnu rẹ̀ si wa li oju awọn ọba Persia, lati tun mu wa yè, lati gbe ile Ọlọrun wa duro, ati lati tun ahoro rẹ̀ ṣe, ati lati fi odi kan fun wa ni Juda, ati ni Jerusalemu.

10. Njẹ nisisiyi, Ọlọrun wa, kili awa o wi lẹhin eyi? nitoriti awa ti kọ̀ aṣẹ rẹ silẹ,

11. Ti iwọ ti pa lati ẹnu awọn woli iranṣẹ rẹ wá, wipe, Ilẹ na ti ẹnyin nlọ igbà nì, ilẹ alaimọ́ ni, fun ẹgbin awọn enia ilẹ na, fun irira wọn, pẹlu ìwa-ẽri ti nwọn fi kun lati ikangun kan de ekeji.

12. Njẹ nitorina ki ẹnyin ki o máṣe fi ọmọ nyin obinrin fun ọmọ wọn ọkunrin, bẹ̃ni ki ẹnyin ki o máṣe mu ọmọ wọn obinrin fun ọmọ nyin ọkunrin, bẹ̃ni ki ẹnyin ki o máṣe wá alafia wọn tabi irọra wọn titi lai: ki ẹnyin ki o le ni agbara, ki ẹ si le ma jẹ ire ilẹ na, ki ẹ si le fi i silẹ fun awọn ọmọ nyin ni ini titi lai.

Esr 9