24. Ẹni tí ó pè yín yóo ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé olóòótọ́ ni.
25. Ẹ̀yin ará, ẹ máa gbadura fún wa.
26. Ẹ fi ìfẹnukonu mímọ́ kí gbogbo àwọn onigbagbọ.
27. Mo fi Oluwa bẹ̀ yín, ẹ ka ìwé yìí fún gbogbo ìjọ.
28. Kí oore-ọ̀fẹ́ Oluwa wa Jesu Kristi kí ó wà pẹlu yín.