Orin Dafidi 97:6-10 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀;gbogbo orílẹ̀-èdè sì ń wo ògo rẹ̀.

7. Ojú ti gbogbo àwọn tí ń bọ oriṣa,àwọn tí ń fi ère lásánlàsàn yangàn;gbogbo oriṣa ní ń foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀.

8. Àwọn ará Sioni gbọ́, inú wọn dùn.Àwọn ará ìlú Juda sì ń yọ̀,nítorí ìdájọ́ rẹ, OLUWA.

9. Nítorí ìwọ OLUWA ni Ọ̀gá Ògo,o ju gbogbo ayé lọ,a gbé ọ ga ju gbogbo oriṣa lọ.

10. Ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn OLUWA, ẹ kórìíra ibi;OLUWA á máa dá ẹ̀mí àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sí,a sì máa gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.

Orin Dafidi 97