Orin Dafidi 83:6-11 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Àwọn ará Edomu, ati àwọn ọmọ Iṣimaeli,àwọn ará Moabu, ati àwọn ọmọ Hagiri,

7. àwọn ará Gebali, àwọn ọmọ Amoni, ati àwọn ọmọ Amaleki,àwọn ará Filistia ati àwọn tí ń gbé Tire.

8. Àwọn ará Asiria pàápàá ti dara pọ̀ mọ́ wọn;àwọn ni alátìlẹ́yìn àwọn ọmọ Lọti.

9. Ṣe wọ́n bí o ti ṣe àwọn ará Midiani,bí o ti ṣe Sisera ati Jabini ni odò Kiṣoni,

10. àwọn tí o parun ní Endori,tí wọ́n di ààtàn lórí ilẹ̀.

11. Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí o ti ṣe Orebu ati Seebu;ṣe àwọn ìjòyè wọn bí o ti ṣe Seba ati Salumuna,

Orin Dafidi 83