Orin Dafidi 78:40-47 BIBELI MIMỌ (BM)

40. Ìgbà mélòó ni wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i ninu ijù,tí wọ́n sì bà á lọ́kàn jẹ́ ninu aṣálẹ̀!

41. Wọ́n dán an wò léraléra,wọ́n sì mú Ẹni Mímọ́ Israẹli bínú.

42. Wọn kò ranti agbára rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ranti ọjọ́ tí ó rà wọ́n pada lọ́wọ́ ọ̀tá;

43. nígbà tí ó ṣe iṣẹ́ abàmì ní ilẹ̀ Ijipti,tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní oko Soani.

44. Ó sọ omi odò wọn di ẹ̀jẹ̀,tí wọn kò fi lè mu omi wọn.

45. Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin sí wọn tí ó jẹ wọ́n,ati ọ̀pọ̀lọ́ tí ó pa wọ́n run.

46. Ó mú kí kòkòrò jẹ èso ilẹ̀ wọn;eṣú sì jẹ ohun ọ̀gbìn wọn.

47. Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́;ó sì fi òjò dídì run igi Sikamore wọn.

Orin Dafidi 78