Orin Dafidi 78:14-18 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ó fi ìkùukùu ṣe atọ́nà wọn ní ọ̀sán,ó fi ìmọ́lẹ̀ iná tọ́ wọn sọ́nà ní gbogbo òru.

15. Ó la àpáta ni aṣálẹ̀,ó sì fún wọn ní omi mu lọpọlọpọ bí ẹni pé láti inú ibú.

16. Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta;ó sì mú kí ó ṣàn bí odò.

17. Sibẹsibẹ wọn ò dẹ́kun ẹ̀ṣẹ̀ dídá;wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo ninu aṣálẹ̀.

18. Wọ́n dán Ọlọrun wò ninu ọkàn wọn,wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóo tẹ́ ìfẹ́ ọkàn wọn lọ́rùn.

Orin Dafidi 78