Orin Dafidi 38:2-11 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Nítorí pé ọfà rẹ ti wọ̀ mí lára,ọwọ́ rẹ sì ti bà mí.

3. Kò sí ibìkan tí ó gbádùn ní gbogbo ara minítorí ibinu rẹ;kò sì sí alaafia ninu gbogbo egungun mi,nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi.

4. Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti bò mí lórí mọ́lẹ̀;ó rìn mí mọ́lẹ̀ bí ẹrù ńlátí ó wúwo jù fún mi.

5. Ọgbẹ́ mi ń kẹ̀, ó sì ń rùn,nítorí ìwà òmùgọ̀ mi,

6. Ìbànújẹ́ dorí mi kodò patapata,mo sì ń ṣọ̀fọ̀ kiri tọ̀sán-tòru.

7. Gbogbo ẹ̀gbẹ́ mi ń gbóná fòò,kò sí ibìkan tí ó gbádùn lára mi.

8. Àárẹ̀ mú mi patapata, gbogbo ara sì wó mi;mò ń kérora nítorí ẹ̀dùn ọkàn mi.

9. OLUWA, gbogbo ìfẹ́ ọkàn mi ni o mọ̀,ìmí ẹ̀dùn mi kò sì pamọ́ fún ọ.

10. Àyà mi ń lù pì pì pì, ó rẹ̀ mí láti inú wá;ojú mi sì ti di bàìbàì.

11. Àwọn ọ̀rẹ́ ati àwọn ẹlẹgbẹ́ mi takété sí mi nítorí àrùn mi,àwọn ẹbí mi sì dúró lókèèrè réré.

Orin Dafidi 38