Orin Dafidi 35:26-28 BIBELI MIMỌ (BM)

26. Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí ń yọ̀ pé ìpọ́njú dé bá mi;kí ìdààmú bá wọn;bá mi da aṣọ ìtìjú ati ẹ̀tẹ́ bo àwọn tí ń gbé àgbéré sí mi.

27. Kí àwọn tí ń wá ìdáláre mimáa hó ìhó ayọ̀, kí inú wọn sì máa dùn,kí wọ́n máa wí títí ayé pé,“OLUWA tóbi,inú rẹ̀ dùn sí alaafia àwọn iranṣẹ rẹ̀.”

28. Nígbà náà ni n óo máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,n óo sì máa yìn ọ́ tọ̀sán-tòru.

Orin Dafidi 35