Orin Dafidi 145:12-16 BIBELI MIMỌ (BM)

12. láti mú àwọn eniyan mọ agbára rẹ,ati ẹwà ògo ìjọba rẹ.

13. Ìjọba ayérayé ni ìjọba rẹ,yóo sì máa wà láti ìran dé ìran.Olóòótọ́ ni OLUWA ninu gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀,olóore ọ̀fẹ́ sì ni ninu gbogbo ìṣe rẹ̀.

14. OLUWA gbé gbogbo àwọn tí ń ṣubú lọ dìde,ó sì gbé gbogbo àwọn tí a tẹrí wọn ba nàró.

15. Ojú gbogbo eniyan ń wò ọ́,o sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àsìkò.

16. Ìwọ la ọwọ́ rẹ,o sì tẹ́ gbogbo ẹ̀dá alààyè lọ́rùn.

Orin Dafidi 145