Orin Dafidi 138:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. N óo máa yìn ọ́ tọkàntọkàn OLUWA,lójú àwọn oriṣa ni n óo máa kọrin ìyìn sí ọ.

2. Ní ìtẹríba, n óo kọjú sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ,n óo sì máa yin orúkọ rẹ,nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ rẹ,nítorí pé o gbé ọ̀rọ̀ rẹ ati orúkọ rẹ ga ju ohunkohun lọ.

3. Ní ọjọ́ tí mo ké pè ọ́, o dá mi lóhùn,o sì fún mi ní agbára kún agbára.

4. OLUWA, gbogbo ọba ayé ni yóo máa yìn ọ́,nítorí pé wọ́n ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.

Orin Dafidi 138