Orin Dafidi 119:29-33 BIBELI MIMỌ (BM)

29. Mú ìwà èké jìnnà sí mi,kí o sì fi oore ọ̀fẹ́ kọ́ mi ní òfin rẹ.

30. Mo ti yan ọ̀nà òtítọ́,mo ti fi ọkàn sí òfin rẹ.

31. Mo pa òfin rẹ mọ́, OLUWA,má jẹ́ kí ojú ó tì mí.

32. N óo yára láti pa òfin rẹ mọ́,nígbà tí o bá mú òye mi jinlẹ̀ sí i.

33. OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ,n óo sì pa wọ́n mọ́ dé òpin.

Orin Dafidi 119