Orin Dafidi 118:15-21 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ẹ gbọ́ orin ayọ̀ ìṣẹ́gun,ninu àgọ́ àwọn olódodo.“Ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ti ṣe iṣẹ́ agbára ńlá.

16. A gbé ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ga,ọwọ́ ọ̀tún OLUWA ti ṣe iṣẹ́ agbára ńlá!”

17. N ò ní kú, yíyè ni n óo yè,n óo sì máa fọnrere nǹkan tí OLUWA ṣe.

18. OLUWA jẹ mí níyà pupọ,ṣugbọn kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.

19. Ṣí ìlẹ̀kùn òdodo fún mi,kí n lè gba ibẹ̀ wọlé,kí n sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA.

20. Èyí ni ẹnu ọ̀nà OLUWA;àwọn olódodo yóo gba ibẹ̀ wọlé.

21. Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí pé o gbọ́ ohùn mi,o sì ti di olùgbàlà mi.

Orin Dafidi 118