Luku 1:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Nígbà tí ó yá, ó kan ìpín àwọn Sakaraya láti wá ṣe iṣẹ́ alufaa níwájú Ọlọrun ninu Tẹmpili.

9. Gẹ́gẹ́ bí àṣà àwọn alufaa, Sakaraya ni ìbò mú láti sun turari ninu iyàrá Tẹmpili Oluwa.

10. Gbogbo àwọn eniyan ń gbadura lóde ní àkókò tí ó ń sun turari.

11. Angẹli Oluwa kan bá yọ sí i, ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún pẹpẹ turari.

12. Nígbà tí Sakaraya rí i, ó ta gìrì, ẹ̀rù bà á.

Luku 1