Kronika Kinni 10:3-6 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ogun gbóná janjan yí Saulu ká, àwọn tafàtafà rí i, wọ́n ta á lọ́fà, ó sì fara gbọgbẹ́,

4. Saulu ba sọ fún ọdọmọkunrin tí ń ru ihamọra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì gún mi pa, kí àwọn aláìkọlà ará Filistia má baà fi mi ṣẹ̀sín.” Ṣugbọn ẹni tí ń ru ihamọra rẹ̀ kọ̀, nítorí pe ẹ̀rù bà á; nítorí náà, Saulu fa idà ara rẹ̀ yọ, ó sì ṣubú lé e.

5. Nígbà tí ọdọmọkunrin náà rí i pé Saulu kú, òun náà ṣubú lé idà rẹ̀, ó sì kú.

6. Bẹ́ẹ̀ ni Saulu, àwọn ọmọ rẹ̀ mẹtẹẹta ati àwọn ará ilé rẹ̀ ṣe kú papọ̀.

Kronika Kinni 10