Kọrinti Kinni 9:3-7 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ìdáhùn mi nìyí fún àwọn tí wọn ń rí wí sí mi.

4. Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti jẹ ati láti mu ni?

5. Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti máa mú aya lọ́wọ́ ninu ìrìn àjò wa gẹ́gẹ́ bí àwọn aposteli yòókù ati àwọn arakunrin Oluwa ati Peteru?

6. Àbí èmi ati Banaba nìkan ni a níláti máa ṣiṣẹ́ bọ́ ara wa?

7. Ta ló jẹ́ ṣe iṣẹ́ ọmọ-ogun tí yóo tún máa bọ́ ara rẹ̀? Ta ló jẹ́ dá oko láì má jẹ ninu èso rẹ̀? Ta ló jẹ́ máa tọ́jú aguntan láìmu ninu wàrà aguntan tí ó ń tọ́jú?

Kọrinti Kinni 9