Jeremaya 3:21-24 BIBELI MIMỌ (BM)

21. A gbọ́ ohùn kan lórí àwọn òkè gíga,ẹkún ati ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọkunrin Israẹli ni.Nítorí wọ́n ti yapa kúrò lójú ọ̀nà wọn;wọ́n ti gbàgbé OLUWA Ọlọrun wọn.

22. Ẹ yipada, ẹ̀yin alaiṣootọ ọmọ,n óo mú aiṣootọ yín kúrò.“Wò wá! A wá sọ́dọ̀ rẹ,nítorí ìwọ ni OLUWA Ọlọrun wa.

23. Nítòótọ́, ẹ̀tàn ni àwọn òkè,ati gbogbo ohun tí wọn ń lọ ṣe níbẹ̀;dájúdájú lọ́dọ̀ OLUWA Ọlọrun wa ni ìgbàlà Israẹli wà.

24. Ṣugbọn láti ìgbà èwe wa ni ohun ìtìjú yìíti pa gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá wa ṣiṣẹ́ fún run:ẹran ọ̀sìn wọn, ati agbo mààlúù wọn,àwọn ọmọ wọn lọkunrin ati lobinrin.

Jeremaya 3