13. OLUWA, ìwọ ni Israẹli gbójú lé,ojú yóo ti gbogbo àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀.A óo kọ orúkọ àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀ sórí ilẹ̀,yóo sì parẹ́,nítorí pé wọ́n ti kọ OLUWA, orísun omi ìyè, sílẹ̀.
14. Wò mí sàn, OLUWA, ara mi yóo sì dá,gbà mí, n óo sì bọ́ ninu ewu.Nítorí pé ìwọ ni mò ń yìn.
15. Wò ó! Wọ́n ń bi mí pé,“Níbo ni gbogbo ìhàlẹ̀ OLUWA já sí?Jẹ́ kí ó ṣẹ, kí á rí i!”
16. N kò bẹ̀bẹ̀ pé kí o rán ibi sí wọn,bẹ́ẹ̀ ni n kò fẹ́ ọjọ́ ibi fún wọn.OLUWA, o mọ̀ bẹ́ẹ̀.Ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde kò tún lè ṣàjèjì sí ọ.
17. Má di ohun ẹ̀rù fún mi,nítorí ìwọ ni ibi ààbò mi ní ọjọ́ ibi.