Jẹnẹsisi 49:17-25 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Dani yóo dàbí ejò lójú ọ̀nà,ati bíi paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,tí ń bu ẹṣin ní gìgísẹ̀ jẹ,kí ẹni tí ó gùn ún lè ṣubú sẹ́yìn.

18. Mo dúró de ìgbàlà rẹ, Oluwa.

19. Àwọn olè yóo máa kó Gadi lẹ́rù,ṣugbọn bí wọ́n ti ń kó o,bẹ́ẹ̀ ni yóo sì máa gbà á pada.

20. Aṣeri yóo máa rí oúnjẹ dáradára mú jáde ninu oko rẹ̀,oúnjẹ ọlọ́lá ni yóo máa ti inú oko rẹ̀ jáde.

21. Nafutali dàbí àgbọ̀nrín tí ń sáré káàkiri,tí ó sì ní àwọn ọmọ tí ó lẹ́wà.

22. Josẹfu dàbí igi eléso tí ó wà lẹ́bàá odò,àwọn ẹ̀ka rẹ̀ nà mọ́ ara ògiri.

23. Àwọn tafàtafà gbógun tì í kíkankíkan,wọ́n ń ta á lọ́fà, wọ́n sì ń dà á láàmú gidigidi,

24. sibẹsibẹ ọrùn rẹ̀ kò mì,apá rẹ̀ sì ń lágbára sí i.Agbára Ọlọrun Jakọbu ni ó fún apá rẹ̀ ní okun,(ní orúkọ Olùṣọ́-aguntan náà,tí í ṣe Àpáta ààbò Israẹli),

25. Ọlọrun baba rẹ yóo ràn ọ́ lọ́wọ́.Ọlọrun Olodumare yóo rọ òjò ibukun sórí rẹ láti òkè ọ̀run wá,yóo sì fún ọ ní ibukun omi tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀,ati ọpọlọpọ ọmọ ati ọpọlọpọ ẹran ọ̀sìn.

Jẹnẹsisi 49