Isikiẹli 35:3-7 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Wí fún un pé OLUWA Ọlọrun ní,‘Wò ó! Mo lòdì sí ọ,ìwọ Òkè Seiri.N óo nawọ́ ibinu sí ọ,n óo sọ ọ́ di ahoro ati aṣálẹ̀.

4. N óo sọ àwọn ìlú rẹ di aṣálẹ̀ìwọ pàápàá yóo sì di ahoro;o óo wá mọ̀ pé èmi ni OLUWA.

5. “ ‘Nítorí pé ò ń fẹ́ràn ati máa ṣe ọ̀tá lọ títí, o sì fa àwọn ọmọ Israẹli fún ogun pa nígbà tí ìṣòro dé bá wọn, tí wọn ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

6. Nítorí náà, OLUWA Ọlọrun ní, mo fi ara mi búra pé, n óo fi ọ́ fún ikú pa, ikú yóo máa lépa rẹ, nítorí pé apànìyàn ni ọ́; ikú yóo máa lépa ìwọ náà.

7. N óo sọ òkè Seiri di aṣálẹ̀ ati ahoro. N óo pa gbogbo àwọn tí ń lọ tí ń bọ̀ níbẹ̀.

Isikiẹli 35