Ẹkún Jeremaya 5:16-21 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Adé ti ṣíbọ́ lórí wa!A gbé! Nítorí pé a ti dẹ́ṣẹ̀,

17. nítorí náà, ọkàn wa ti rẹ̀wẹ̀sì;ojú wa sì ti di bàìbàì.

18. Nítorí òkè Sioni tí ó di ahoro;tí àwọn ọ̀fàfà sì ń ké lórí rẹ̀.

19. Ṣugbọn ìwọ OLUWA ni ó jọba títí ayé,ìtẹ́ rẹ sì wà láti ìrandíran.

20. Kí ló dé tí o fi gbàgbé wa patapata?Tí o sì kọ̀ wá sílẹ̀ fún ìgbà pípẹ́?

21. Mú wa pada sọ́dọ̀ ara rẹ, OLUWA,kí á lè pada sí ipò wa.Mú àwọn ọjọ́ àtijọ́ wa pada.

Ẹkún Jeremaya 5