Daniẹli 4:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọba Babiloni ranṣẹ sí gbogbo àwọn eniyan, ati gbogbo orílẹ̀-èdè ati ẹ̀yà ní gbogbo ayé, pé:“Kí alaafia wà pẹlu yín!

2. Ó tọ́ lójú mi láti fi àmì ati iṣẹ́ ìyanu, tí Ọlọrun tí ó ga jùlọ ṣe fún mi, hàn.

3. “Iṣẹ́ rẹ̀ tóbi gan-an!Iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sì lágbára lọpọlọpọ!Títí ayérayé ni ìjọba rẹ̀,àtìrandíran rẹ̀ ni yóo sì máa jọba.

4. “Èmi, Nebukadinesari wà ninu ìdẹ̀ra ní ààfin mi, nǹkan sì ń dára fún mi.

5. Mo lá àlá kan tí ó bà mí lẹ́rù. Èrò ọkàn mi ati ìran tí mo rí lórí ibùsùn mi kó ìdààmú bá mi.

Daniẹli 4