Sefanáyà 1:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúròlórí ilẹ̀ náà pátapáta,”ni Olúwa wí.

3. “Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹrankokúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojúọ̀run kúrò àti ẹja inú òkun, àtiohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọnènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”ni Olúwa wí

4. “Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Júdààti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jérúsálẹ́mù.Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Báálì, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣàpẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5. àti àwọn tí wọn ń foríbalẹ̀ tí wọnń sin ogun ọ̀run lórí òrùlé.Àwọn tí wọn ń sìn, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,tí wọ́n sì ń fi Mólékì búra.

6. Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.

Sefanáyà 1