4. Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbérága jáde;gbogbo àwọn olùṣebúburúkún fún ìṣògo.
5. Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn Rẹ túútúú, Olúwa:wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní Rẹ̀ lójú.
6. Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò,wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba,
7. Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i;Ọlọ́run Jákọ́bù kò sì kíyèsí i.”
8. Kíyèsí i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyànẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?