Sáàmù 83:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn Rẹ;wọn gbìmọ̀ lòdì sí àwọn tí ó fẹ.

4. Wọn wí pé, “wá,” ẹ jẹ́ kí a pa wọn run bí orílẹ̀ èdè,kí orúkọ Ísírẹ́lì ma bá a sí ní ìrántí mọ́.

5. Wọn gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan;wọ́n ṣe àdéhùn láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ

6. Àgọ́ Édómù àti ti àwọn ara Íṣímaélì,tí Móábù àti ti Hágárì

7. Gébálì, Ámónì àti Ámálékì,Fílítísitíà, pẹ̀lú àwọn ènìyàn Tirẹ̀.

8. Áṣurí pẹ̀lú tí darapọ̀ mọ́ wọnláti ràn àwọn ọmọ Lọ́ọ̀tì lọ́wọ́. Sela

9. Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Mídíánìbí o ti ṣe sí Sísérà àti Jábínì ní òdò Kíṣíónì,

Sáàmù 83