Sáàmù 81:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúro ní èjìká yín,a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.

7. Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là,mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá,mo dán an yín wò ní odò Méríbà. Sela

8. “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Ísírẹ́lì.

9. Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrin yín;ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.

10. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run Rẹ,ẹni tí ó mú un yín jáde láti Éjíbítì.Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.

11. “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;Ísírẹ́lì kò ní tẹríba fún mi.

12. Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọnláti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.

Sáàmù 81