Sáàmù 73:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀ òdì nítiìnilára, wọn ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.

9. Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀runahọ́n wọn gba ipò ayé.

10. Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọnwọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

11. Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?Ọ̀gá ògo ha ní ìmọ̀ bí?”

12. Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyíènìyàn asán, wọn ń pọ̀ ní ọrọ̀.

13. Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́sẹ̀.

14. Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;a sì ń jẹ mí níyà ní gbogbo òwúrọ̀.

15. Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”Èmi ó ṣẹ̀sí ìran àwọn ọmọ Rẹ̀.

16. Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,O jẹ́ ìnilára fún mi.

17. Tí tí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;Nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi,

Sáàmù 73