6. Má ṣe dójú tì àwọn tí ó ní ìrètí nínú Rẹnítorí mi, Olúwa, Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun;Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,Ọlọ́run Ísírẹ́lì.
7. Nítorí Rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,ìtìjú sì bo ojú mi.
8. Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9. Nítorí ìtarà ilé Rẹ jẹ mí run,àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10. Nígbà tí mo sunkúntí mo sì ń fi ààwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyàèyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11. Nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,àwọn ènìyàn ń pòwe mọ́ mi.
12. Àwọn tí ó jòkòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.