4. Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìíwọn ju irun orí mi; lọpúpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí,àwọn tí ń wá láti pa mí runA fi ipá mú miláti san ohun tí èmi kò jí.
5. Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú Rẹ.
6. Má ṣe dójú tì àwọn tí ó ní ìrètí nínú Rẹnítorí mi, Olúwa, Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun;Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,Ọlọ́run Ísírẹ́lì.
7. Nítorí Rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,ìtìjú sì bo ojú mi.
8. Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9. Nítorí ìtarà ilé Rẹ jẹ mí run,àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10. Nígbà tí mo sunkúntí mo sì ń fi ààwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyàèyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;