Sáàmù 59:14-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Wọ́n padà ní àsálẹ́,wọn ń gbó bí àwọn ajáwọ́n ń rìn ìlú náà káàkiri.

15. Wọ́n ń rín kiri fún oúnjẹwọn sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.

16. Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára Rẹ,ń ó kọrin ìfẹ́ Rẹ ní òwúrọ̀;nítorí ìwọ ni ààbò mi,ibi ìsádì mi ní ìgbà ìpọ́njú.

17. Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ;ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

Sáàmù 59