Sáàmù 18:28-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mikí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.

29. Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Rẹ̀, èmi ṣare la ogun lọ;pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan

30. Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà Rẹ̀ pé,a ti rídìí ọ̀rọ̀ Olúwaòun ni àpáta ààbòfún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.

31. Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa?Ta ní àpátà bí kò ṣe Olúwa wa?

Sáàmù 18