Sáàmù 149:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ fi ìyìn Olúwa.Ẹ kọrin titun sí Olúwa.Ẹ yìn ín ní àwùjọ àwọn ènìyàn mímọ́

2. Jẹ́ kí Ísírẹ́lì kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá ajẹ́ kí àwọn ọmọ Síónì kí ó níayọ̀ nínú ọba wọn.

3. Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ Rẹ̀jẹ́ kí wọn kí ó fi ohun èlò orin kọrin ìyìn sí i.

4. Nítorí Olúwa ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn Rẹ̀ó fi ìgbàlà dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé

Sáàmù 149