Sáàmù 147:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Olúwa ní ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀,sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú Rẹ̀.

12. Yin Olúwa, ìwọ Jérúsálẹ́mùyin Ọlọ́run Rẹ̀, ìwọ Síónì.

13. Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ìbodè Rẹ̀ lágbára;Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ Rẹ̀ nínú Rẹ

14. Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè Rẹ̀òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.

15. Òun sì rán àṣẹ Rẹ̀ sí ayéọ̀rọ̀ Rẹ̀ sáré tete.

16. Ó fi sino fún ni bi irun àgùntànó sì fọ́n ìrì idídì ká bí eérú

17. Ó rọ òjò yìnyín Rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ta ni ó lè dúró níwájú òtútù Rẹ̀

18. Ó rán ọ̀rọ̀ Rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ó mú kí afẹ́fẹ́ Rẹ̀ fẹ́ó sì mú odò Rẹ̀ sàn.

Sáàmù 147