Sáàmù 119:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Èmi yóò gbọ́ràn sí asẹ Rẹ̀:Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátapáta.

9. Báwo ni àwọn èwe ènìyàn yóò ti ṣe pa ọ̀nà Rẹ̀ mọ́?Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

10. Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mimá ṣe jẹ́ kí èmi yàpa kúrò nínú àṣẹ̀ Rẹ.

11. Èmi ti pa ọ̀rọ̀ Rẹ mọ́ ní ọkàn mikí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ

12. Ìyìn ni fún Olúwa;kọ́ mi ní àsẹ Rẹ.

13. Pẹ̀lú ètè mi èmi tún sírògbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu Rẹ.

14. Èmi yọ̀ nínú títẹ̀lé òrin Rẹbí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọlá ńlá.

15. Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà Rẹèmi sì kíyèsí ọ̀nà Rẹ

16. Inú mi dùn sí àṣẹ Rẹ;èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà Rẹ.

17. Ṣe rere sí ìránṣẹ́ Rẹ, èmi yóò sì wà láàyè;èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

Sáàmù 119