Sáàmù 118:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Wọn gbá yìnìn yí mí ká bí oyin,ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún;ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.

13. Ìwọ tì mi gidigidi kí ń lè subú,ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.

14. Olúwa ni agbára àti orin mi;ó si di ìgbàlà mi.

15. Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:“ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!

16. Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbé ga;ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”

Sáàmù 118