Sáàmù 115:4-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Òrìṣà fàdákà àti wúrà,iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn

5. Wọn ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ̀rọ̀,wọn ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.

6. Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ràn:wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọ́n kò fi gbóòórùn

7. Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó,wọ́n ní ẹṣẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn;bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.

8. Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn;gẹ́gẹ́ bẹ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ Rẹ̀ lé wọn.

9. Ìwọ Ísírẹ́lì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn

10. Ẹ yin ilé Árónì, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn

11. Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.

12. Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Ísírẹ́lì;yóò bùkún ilé Árónì.

Sáàmù 115