Òwe 16:6-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nípaṣẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣètùtù ẹ̀ṣẹ̀nípaṣẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.

7. Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn,yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn-án bá a gbé ní àlàáfíà.

8. Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodoju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú.

9. Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.

10. Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa inú síiẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ gbé ẹ̀bi fún ara rẹ̀.

11. Òdiwọ̀n àti òṣùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.

12. Àwọn ọba kórìírà ìwà àìtọ́nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.

Òwe 16