Òwe 15:23-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó báa muọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!

24. Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọgbọ́nláti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú.

25. Olúwa fa ilé onígbéraga ya lulẹ̀,Ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó mọ́ láìyẹ̀.

26. Olúwa kórìíra èrò ènìyàn búburú,

27. Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.

28. Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wòṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.

29. Olúwa jìnnà sí ènìyàn búburúṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.

Òwe 15