Orin Sólómónì 5:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Èmi sí ilẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn

7. Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ ìlú rí mibí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.Wọ́n nà mí, wọ́n ṣá mi lọ́gbẹ́;wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!

8. Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù, mo bẹ̀ yínbí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?Ẹ wí fún un pé àìṣàn ìfẹ́ ń ṣe mi.

9. Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tó kù lọÌwọ arẹwà jùlọ láàárin àwọn obìnrin?Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tó kù lọtí ìwọ fi ń rọ̀ wá bẹ́ẹ̀?

10. Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́nó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ.

Orin Sólómónì 5