Onídájọ́ 5:26-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Ó na ọwọ́ rẹ̀ mú ìṣó àgọ́,ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú òòlù awọ gbẹ́nàgbẹ́nà.Ó kan Ṣísérà mọ́lẹ̀ pẹ̀lú òòlù ọwọ́ rẹ̀, ó fọ́ ọ ní orí,Ó kàn ẹ̀bátí rẹ̀ mọ́lẹ̀ sinsiǹ.

27. Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ó ṣubú; ó dúbúlẹ̀.Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wó lulẹ̀;ní ibi tí ó gbé wólẹ̀ sí, níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú.

28. “Ìyá Ṣísérà yọjú láti ojú fèrèsé,ó sì kígbe, ó kígbe ní ojú fèrèsé ọlọ́nà pé,‘Èése tí kẹ̀kẹ́ ẹsin rẹ fi pẹ́ bẹ́ẹ̀ láti dé?Èéṣe tí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ẹsin rẹ̀ fí dúró lẹ́yìn?’

29. Àwọn amòye obìnrin rẹ̀ dá a lóhùn;àní òun náà pẹ̀lú ti dá ara rẹ̀ lóhùn pé,

Onídájọ́ 5