Onídájọ́ 11:33-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní àpa tán láti Áróérì títí dé agbègbè Mínítì, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Kérámímù. Báyìí ni Ísírẹ́lì ti ṣẹ́gun àwọn ará Ámónì.

34. Nígbà tí Jẹ́fítà padà sí ilé rẹ̀ ní Mísípà, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú taboríìnì àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.

35. Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le ṣẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”

36. Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀ṣan fún ọ lára àwọn ọ̀ta rẹ, àwọn ará Ámónì.

37. Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láàyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n ṣunkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúndíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”

Onídájọ́ 11