Nọ́ḿbà 7:80-84 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

80. Àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì méwàá tí ó kún fún tùràrí;

81. Akọ ọ̀dọ́ màlúù kan àgbò kan, àti akọ ọ̀dọ́ àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun;

82. Akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀;

83. Màlúù méjì, àgbò márùn-ún, akọ ewúrẹ́ márùn-ún àti akọ ọ̀dọ́ àgùntàn ọlọ́dún kan márùn-ún, wọn ó fi rú ẹbọ àlàáfíà. Èyí ni ọrẹ Áhírà ọmọ Énánì.

84. Wọ̀nyí ni ọrẹ tí àwọn olórí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì mú wá fún ìyàsímímọ́ pẹpẹ nígbà tí wọ́n ta òróró sí i lórí: àwo fàdákà méjìlá, àwokòtò méjìlá, àwo wúrà méjìlá.

Nọ́ḿbà 7