Nọ́ḿbà 3:27-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Ti Kóhátì ní ìdílé Ámírámù, Ísíhárì, Hébírónì àti Yúsíélì, wọ̀nyí ni ìran Kóhátì

28. Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta, (8,600) tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.

29. Àwọn ìdílé Kóhátì yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúṣù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.

30. Olórí àwọn ìdílé Kóhátì ni Élísáfì ọmọ Yúsíélì.

31. Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tabílì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.

Nọ́ḿbà 3