Nehemáyà 9:12-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ní ọ̀sán ìwọ daríi wọn pẹ̀lú òpó ìkúùkú àti ní òru ni ìwọ daríi wọn pẹ̀lú òpó iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.

13. “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Ṣínáì; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.

14. Ìwọ mú ọjọ́ Ìsinmi rẹ mímọ́ di mímọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ọ Mósè ìránṣẹ́ẹ̀ rẹ.

15. Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òrùngbẹ o fún wọn ní omi láti inú àpáta; ó sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn.

Nehemáyà 9