Mátíù 5:27-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Ẹ̀yin ti gbọ́ bí òfin ti wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.’

28. Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá wo obìrinrin kan ní ìwòkuwò, ti bà a ṣe panṣágà ná ní ọkàn rẹ̀.

29. Bí ojú rẹ ọ̀tún bá mú ọ dẹ́sẹ̀, yọ ọ́ jáde, kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó sàn kí ẹ̀ya ara rẹ kan ṣègbé, ju kí a gbé gbogbo ara rẹ jù sínú iná ọ̀run àpáàdì.

30. Bí ọwọ́ rẹ ọ̀tún bá mú ọ dẹ́ṣẹ̀ gé e kúrò, kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó sàn kí ẹ̀ya ara rẹ kan ṣègbé ju kí gbogbo ara rẹ lọ sínú iná ọ̀run àpáàdì.

31. “A ti wí pẹ̀lú pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀ gbọdọ̀ fún un ní ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀.’

32. Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀, àfi nítorí àgbèrè, mú un se àgbèrè, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì fẹ́ obìnrin tí a kọ̀ sílẹ̀ ní ìyàwó ṣe àgbèrè.

Mátíù 5