Mátíù 25:29-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ní a ó fún sí i, yóò sí tún ní sí lọ́pọ̀lọpọ̀. Ṣùgbọ́n láti ọwọ́ ẹni tí kò ní ni a ó ti gbà èyí tí ó ní.

30. Nítorí ìdi èyí, gbé aláìlérè ọmọ-ọ̀dọ̀, jù ú sínú òkùnkùn lóde, ibẹ̀ niẹ̀kún òun ìpayínkeke yóò gbé wà.’

31. “Ṣùgbọ́n nígbà ti Ọmọ-Ènìyàn yóò wá nínú ògo rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ańgẹ́lì rẹ̀ nígbà náà ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ ògo ní ọ̀run.

32. Gbogbo orílẹ̀-èdè ni a ó kó jọ níwájú rẹ̀, òun yóò sì ya àwọn ènìyàn ayé sí ọ̀tọ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́ àgùntàn ṣe é ya àgùntàn kúrò lára àwọn ewúrẹ́.

33. Òun yóò sì fi àgùntàn sí ọwọ́ ọ̀tún àti ewúrẹ́ sí ọwọ́ òsì.

Mátíù 25