1. Bí wọ́n ti sún mọ́ Jérúsalẹmu, tí wọ́n dé ìtòòsí ìlú Bẹ́tífágè ní orí òkè Ólífì, Jésù sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì,
2. Ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí ìletò tó wà ni tòòsí yín, ẹ̀yin yóò rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ti wọ́n so pẹ̀lú ọmọ rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Ẹ tú wọn, kí ẹ sì mú wọn wá fún mi.
3. Bí ẹnikẹ́ni bá sì béèrè ìdí tí ẹ fi ń ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ sáà wí pé, Olúwa ní wọn-ọ́n lò, òun yóò sì rán wọn lọ.”