Máàkù 15:27-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Wọ́n sì kan àwọn olè méjì mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú rẹ̀, ọ̀kan lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀, èkejì lọ́wọ́ òsì rẹ̀.

28. Eléyìí mú àṣọtẹ́lẹ̀ ìwé Mímọ́ ṣẹ wí pé, “Wọ́n kà á pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn búburú.”

29. Àwọn tí ń kọjá lọ sì ń fi ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n ń mi orí wọn pẹ̀lú, wọ́n sì ké pé, “Áà! Ìwọ tí yóò wó tẹ́ḿpìlì tí yóò sì tún un kọ́ láàrin ọjọ́ mẹ́ta.

30. Tí ó bá lágbára tó bẹ́ẹ̀, gba ara rẹ là, kí o sì ti orí àgbélébùú sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú.”

Máàkù 15