10. òun mọ̀ pé nítorí ìlara ni àwọn olórí àlùfáà ṣe fà Jésù lé òun lọ́wọ́.
11. Nígbà náà ni àwọn olórí àlùfáà ru ọ̀pọ̀ ènìyàn sókè pé, kí ó kúkú dá Bárábà dá sílẹ̀ fún wọn.
12. Pílátù sì tún béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ẹ̀yin ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe pẹ̀lú ẹni ti ẹ̀yin n pè ní ọba àwọn Júù?”
13. Wọ́n sì tún kígbe sókè pé, “Kàn án mọ àgbélébùú!”
14. Nígbà náà ni Pílátù bi wọn léèrè pé, “Èéṣe? Búburú kí ni ó ṣe?”Wọ́n sì kígbe sókè gidigidi wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú!”