Máàkù 15:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. òun mọ̀ pé nítorí ìlara ni àwọn olórí àlùfáà ṣe fà Jésù lé òun lọ́wọ́.

11. Nígbà náà ni àwọn olórí àlùfáà ru ọ̀pọ̀ ènìyàn sókè pé, kí ó kúkú dá Bárábà dá sílẹ̀ fún wọn.

12. Pílátù sì tún béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ẹ̀yin ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe pẹ̀lú ẹni ti ẹ̀yin n pè ní ọba àwọn Júù?”

13. Wọ́n sì tún kígbe sókè pé, “Kàn án mọ àgbélébùú!”

14. Nígbà náà ni Pílátù bi wọn léèrè pé, “Èéṣe? Búburú kí ni ó ṣe?”Wọ́n sì kígbe sókè gidigidi wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú!”

Máàkù 15