Lúùkù 19:33-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”

34. Wọ́n sì wí pé, “Olúwa ń fẹ́ lò ó.”

35. Wọ́n sì fà á tọ Jésù wá: wọ́n sì tẹ́ ẹ wọ́n sì gbé Jésù kà á.

36. Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.

37. Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olófì, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí;

38. Wí pé, “Olùbùkún ni Ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!”“Àlààáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”

Lúùkù 19